Ìjọba Ìpínlẹ̀ Adamawa ti bẹ̀rẹ̀ síí pín owó ẹgbẹ̀rún lọ́nà ogójì (N40,000) fún àwọn ọmọbìnrin ẹgbẹ̀rún mẹ́rinlèlógún (24,000) tí a fà láti àwọn agbègbè ìjọba ìbílẹ̀ mọ́kanlèlógún (21) ní ìpínlẹ̀ náà, lábẹ́ ètò Ìgbékalẹ̀ Owó Àfikún (CCT) tí a ṣe láti gbé ẹ̀kọ́ àwọn ọmọdébìnrin lárugẹ.
Gómìnà Ahmadu Umaru Fintiri ṣe àgbékalẹ̀ ìdánilẹ́kọ̀ọ́ náà ní Ilé-ẹ̀kọ́ Gíga Gírámà ti Ìjọba, Fufore, níbi tó ti ṣíṣọ́ lójú ètò ẹ̀kọ́ náà.
Ó sọ pé ètò náà wà fún dín dín àwọn òun ìdènà bí owó ẹ̀kọ́ àti láti mú kí àwọn àǹfààní fún àwọn ọmọbìnrin káàkiri ìpínlẹ̀ náà gbòòrò síi.

Gẹ́gẹ́ bí Gómìnà ti sọ, ọkọ̀ọ̀kan nínú àwọn ọmọ wọ̀nyí yóò gba ogójì lọnà ẹgbẹ̀rún (N40,000) ní sáà ìkẹ́kọ́ọ̀ àkọ́kọ́, lẹ́yìn náà ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá (N10,000) ní sáà ìkẹ́kọ́ọ̀ kejì àti ìkẹta, èyí tí yóò mú gbogbo ìrànlọ́wọ́ náà jẹ́ ọgọ́ta lọnà ẹgbẹ̀rún (N60,000).
Ó fí kún wípé olùkópa nínú ètò náà gbọ́dọ̀ ní o kéré jù ìdá márùnlèlàádọ́rin nínú ọgọ́rùn-ún (75%) nínú onka oyè ọjọ́ tó fí ń ré ilé-ìwé.
Comments are closed.