Take a fresh look at your lifestyle.

Orílè-èdè Nàìjíríà  Ṣe Ìlérí Ifiokan Balẹ  Pẹ̀lú  Orílè-èdè Morocco Lórí Ìkún Omi Tó Ń Búburú

23

Ìjọba Orílè-èdè Nàìjíríà ti fi ìbánikẹ́dùn àti ìfọwọ́sowọ́pọ̀ hàn sí Orílẹ̀-èdè Morocco lẹ́yìn ìkún omi tó burú jáì ní àwọn agbègbè àríwá orílẹ̀-èdè náà tó ti pa ẹ̀mí ènìyàn, àwọn ìdílé tó ti kúrò nílé, tó sì ti ba àwọn ètò ìṣiṣẹ́ tó ṣe pàtàkì jẹ́.

Nínú gbólóhùn kan láti ọwọ́ agbẹnusọ fún Ilé Iṣẹ́ Àjọ Àgbáyé, Kimiebi Ebienfa, Orílè-èdè Nàìjíríà sọ wí pè ó jẹ ohun banújẹ́ gidigidi nípa ìjìyà ènìyàn àti àdánù ohun ìní, ó sì dúró ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú Morocco ní àkókò ìṣòro náà.

Ìjọba Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà gbóríyìn fún ìdáhùn kíákíá ti àwọn aláṣẹ Orílè-èdè Morocco, àwọn òṣìṣẹ́ pajawiri, àti àwọn olùrànlọ́wọ́ nínú iṣẹ́ ìgbàlà àti ìpèsè ìrànlọ́wọ́ fún àwọn agbègbè tó ní ìṣòro ṣe ni akoko náà

Nàìjíríà fi ìgbẹ́kẹ̀lé hàn pé, pẹ̀lú ìsapá orílẹ̀-èdè àti ìfọwọ́sowọ́pọ̀ kárí ayé, àwọn agbègbè tó ní ìṣòro náà yóò padà bọ̀ sípò àti tún kọ́.

Gbólóhùn náà tún fi ìbánikẹ́dùn ọkàn Nàìjíríà hàn sí àwọn ìdílé àwọn tó ní ìṣòro náà, ó sì fi ìbánikẹ́dùn hàn sí gbogbo àwọn tó ní ìṣòro náà.

Comments are closed.

button