Take a fresh look at your lifestyle.

Àwọn Aṣojú rọ Àwọn Oníròyìn Àti Àwọn Olùrànlọ́wọ́ Ìròyìn Láti Mú Kí Òye Wọn Pọ̀ Sí i Lórí Òfin Dígítà

106

Bí ayé ṣe ń lọ sí ìyípadà olóǹkà (Dígítà), Ilé Aṣòfin ti ké sí àwọn oníròyìn àti àwọn olùrànlọ́wọ́ ìròyìn láti kọ́ ìmọ̀ tó lágbára sí i nínú ṣíṣe àyẹ̀wò àwọn òfin olóǹkà àti ìmọ̀-ẹ̀rọ nígbà tí wọ́n bá ń ṣe iṣẹ́ wọn.

‎Alaga Ìgbìmọ̀ Ilé Aṣòfin lórí Ìròyìn àti Àmọ̀ràn Gbogbogbò, Ọ̀gbẹ́ni Akintunde Rotimi, ṣe ìpè náà ní ọjọ́ Ajé nígbà ìpàdé àkojọpọ̀ ọjọ́ kan fún àwọn akọ̀ròyìn ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin ní Abuja.

‎Ayẹyẹ náà, tí a ṣètò pẹ̀lú àjọ ‘Paradigm Initiative Nigeria’, tẹnu mọ́ pàtàkì ìròyìn ìmọ̀-ẹ̀rọ tó dájú lórí àwọn ìròyìn wọn, bíi ààbò dátà, ìwà ọ̀daràn lórí ayélujára, àti ìmọ̀-ẹ̀rọ (AI).

Comments are closed.

button