Àtúnṣe Odò Ńlá Dasin Hausa Ní Ìpínlẹ̀ Adamawa Yóò Tán Ìsòro Omíyalé- Ilé Ìgbìmọ̀ Asòfin Pàrọwà Sí Ìjọba Àpapọ̀
Ilé Ìgbìmọ̀ Asòfin Àgbà ti pàrọwà sí ìjọba àpapọ̀ láti se àtúnṣe Odò ńlá Dasin Hausa ní ìpínlẹ̀ Adamawa, lójúnà àti wá ojútùú sí ìsòro omíyalé ní Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà
Lára àwọn ọ̀nà tí yóò fi òpin sí ìsòro ẹ̀kún omi náà ní síṣe àtúnṣe odò ńlá Benue àti Niger, àti àwọn odò ńlá míràn tí ó já papọ̀ mọ́ odò Lagdo pẹ̀lú ìfọwọ́sowọ́pọ̀ Orílẹ̀-èdè Cameroon.
Ilé ìgbìmọ̀ Asòfin gbé ìgbésẹ̀ náà láti wá ojútùú sí àbádòfin tí sẹ́nétọ̀ Binos Dauda Yaroe láti ìpínlẹ̀ Adamawa gbé jáde, èyí tí ó pèpè fún ọ̀nà àbáyọ sí ìsòro omíyalé láti ara sísí odò ńlá Lagdo ti Orílẹ̀-èdè Cameroon, èyí tí ó ń kó ìpalára bá ará ìlú ní gbogbo ìgbà.
Leave a Reply