Ààrẹ Bola Tinubu ti fi dá àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà lójú nípa ìpinnu ìjọba rẹ̀ láti rí i dájú wí pé àwọn èrè tí a rí nínú àtúnṣe Ìrètí Tuntun ní gbogbo ìpínlẹ̀ àti àwùjọ ní Orílè-èdè Nàìjíríà ni a o ń rí ní gbogbo ìpínlẹ̀ àti àwùjọ ní Nàìjíríà.
Ààrẹ Tinubu ṣe ìdánilójú yìí ni ìlu Abuja níbi ayẹyẹ ìparí ti àtẹ̀jáde kejì ti Àpérò Ìgbìmọ̀ Ọrọ̀-Ajé Orílẹ̀-èdè, tí ó wáyé ní Gbọ̀ngàn Àpérò Ilé Ìgbìmọ̀.
Ó pàṣẹ fún àwọn ọmọ ẹgbẹ́ Ìgbìmọ̀ Ọrọ̀-Ajé Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà (NEC), tí ó ní àwọn Gómìnà ìpínlẹ̀, àwọn òṣìṣẹ́ ìjọba pàtàkì, àti àwọn olùnílò mìíràn tí ó yẹ, láti tún fi ara wọn fún ìmúṣẹ àwọn èrè-ajé tiwantiwa lábẹ́ Àpérò Ìrètí Tuntun.
Ààrẹ sọ wí pé ọlá tí ó ní láti kéde ìpàdé náà ṣí sílẹ̀ pẹ̀lú ìpè tí ó ṣe kedere fún ìṣọ̀kan ète, ìbáwí ìṣúná owó, àti ìgbésẹ̀ tí a ṣètò lábẹ́ Àpérò Ìrètí Tuntun.
Ààrẹ Tinubu, tí Ààrẹ Ìgbìmọ̀ Aṣòfin, Godswill Akpabio, ṣojú fún, sọ wí pé àtúnṣe kì í ṣe ìṣẹ̀lẹ̀ ṣùgbọ́n ìlànà tí ó nílò ìgboyà, sùúrù, àti ìdúróṣinṣin láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn olùnílò.
Ó yin Ààrẹ NEC, Igbákejì Ààrẹ Kashim Shettima fún ìdarí rẹ̀ tí ó dúró ṣinṣin ní Ìgbìmọ̀ Ọrọ̀-Ajé Orílẹ̀-èdè àti fún ṣíṣe amọ̀nà àwọn ìjíròrò pẹ̀lú òye àti àfiyèsí.
NEC rọ àwọn ìjọba ní gbogbo ìpele láti ṣe àfikún sí ètò Ìrètí Tuntun nípa ṣíṣe àgbékalẹ̀ ìmọ̀-ẹ̀rọ àti ọgbọ́n ìmòye àtọwọ́dá láti dúró ní ìdíje nínú ọrọ̀-ajé àgbáyé àti láti ṣètìlẹ́yìn fún ète ọrọ̀-ajé tí ó tó tirinionu dọ́là kan.
Ó rọ àwọn ìpínlẹ̀ láti ṣe òfin owó-orí tí ó báramu láti kojú ọ̀pọ̀lọpọ̀ owó-orí àti láti ṣe àfikún àwọn àtúnṣe owó-orí tí ń lọ lọ́wọ́.
Ìgbìmọ̀ náà tún yin àwọn ìpínlẹ̀ méjìlá tí wọ́n ti ṣe òfin owó-orí tí ó báramu, wọ́n sì gba àwọn ìpínlẹ̀ mẹtala yokun tí wọ́n ní òfin tí ó dúró dè, àti àwọn ìpínlẹ̀ mọkanla tí ó kù tí kò tí ì parí ìlànà náà níyànjú láti yára gba ìgbésẹ̀ náà.