Take a fresh look at your lifestyle.

Olórí Ẹgbẹ́ Ọmọ-ogun Tún Jẹ́rìí sí Ààbò Àwọn Ọmọ-ogun

49

Olórí Ẹgbẹ́ Ọmọ-ogun, Lt. Gen. Waidi Shaibu, ti tún ṣé ìdánilójú pé ẹgbẹ́ ọmọ-ogun Nàìjíríà yóò máa ṣètìlẹ́yìn fún àwọn olórí àti àwọn ọmọ-ogun pẹ̀lú àwọn ètò ìlera tó yẹ, àwọn ohun èlò ìṣiṣẹ́ àti àtìlẹ́yìn àwọn olórí tó yẹ láti jẹ́ kí wọn ṣiṣẹ wọ́n bí iṣẹ́.

‎Gẹ́gẹ́ bí ìkéde tí Olùdarí Àgbà fún Ìbáṣepọ̀ Àwọn Ọmọ-ogun, Colonel Appolonia Anele, Olórí Ẹgbẹ́ Ọmọ-ogun náà fi ìdánilójú náà hàn nígbà tó ń bá àwọn olórí àti àwọn ọmọ-ogun ikọ Ẹgbẹ́ Ọmọ-ogun kéjìdínlógún (18 Brigade) sọ̀rọ̀ ní Baraaki Latin ní Bida, Ìpínlẹ̀ Niger.

‎Nígbà ìgbésẹ̀ náà, Olórí Ẹgbẹ́ Ọmọ-ogun náà sọ pé ààbò àwọn ọmọ-ogun àti àlàáfíà ìdílé wọn ń gba àfiyèsí tó dúró ṣinṣin lábẹ́ ìdarí rẹ̀, ó sì ṣàpèjúwe wọn gẹ́gẹ́ bí àwọn ohun tó ń mú kí iṣẹ́ wọn dára síi àti àṣeyọrí iṣẹ́ wọn.

‎Ó fi dá àwọn ọmọ-ogun lójú pé àtúnṣe sí ipò ìgbésí ayé àti àtìlẹ́yìn ìdílé wọn ṣì ṣe pàtàkì láti mú kí ọkàn àti agbára wọn ṣiṣẹ́ ní ojú ogun.

Comments are closed.

button