Take a fresh look at your lifestyle.

Nàìjíríà Ṣé ìfihàn Ìgbésẹ̀ Àtúnṣe Òfin Tí Ọọ̀ràn-Orí-Ayélujára

Lekan Orenuga

156

Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà tí n ṣé àfihàn ìgbésẹ̀ àtúnṣe tí Òfin Ọọ̀ràn-Orí-Ayélujára, gẹ́gẹ́bí Mínísítà fún ìròyìn àti Àlàyé tí Orílẹ̀-èdè, Mohammed Idris, ṣé ìdánilójú imurasilẹ ìjọba láti ṣiṣẹ́ pẹ̀lú àwọn ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin tí Orílẹ̀-èdè, àwọn oníròyìn, àti àwọn alabaṣepọ pàtàkì mìíràn nínú ìlànà àtúnyẹwò òfin náà tí nlọ́ lọwọ́.

‎ Mínísítà náà kéde èyí lẹ́yìn ìpàdé kán pẹ̀lú Richard Mills, Aṣojú America sí Nàìjíríà, ní ọfiisi rẹ̀ ní Abuja.

‎ Mínísítà náà tẹnumọ pé èròngbà tí ìfọwọ́sowọ́pọ̀ yìí ní láti ṣé ìdàgbàsókè òfin tó ní ifọkanbalẹ tó gbòòrò, tí yóò tún jẹ́ itẹwọgbà fún gbogbo àwọn tó kàn.

‎ Ní iṣáájú, Aṣojú America sí Nàìjíríà, Mills, sọ pé ìpàdé rẹ̀ pẹ̀lú Mínísítà jẹ́ èyí tó nípa, pàápàá lórí àwọn ọran tó jọmọ òmìnira ìròyìn àti ipá pàtàkì tí Ilé-iṣẹ́ ìròyìn àti àlàyé yóò ṣé nínú àtúnyẹwò tí n bọ̀ lórí Òfin àti Irúfin Ayélujára.

‎ O tún ṣé itẹwọgbà àlàyé Mínísítà tí a gbe jade ní Ọjọ́ Òmìnira àwọn Oníròyìn Àgbáyé, èyítí o tún jẹ́ ìfaramọ́ tí ìṣàkóso Ìjọba Ààrẹ Tinubu láti ṣé àtìlẹ́yìn Òmìnira ìròyìn.

Comments are closed.

button