Take a fresh look at your lifestyle.

Àwọn Olókìkí Ọmọ Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà Ṣètọrẹ Fún Iṣẹ́ Ìkọlé Ìkàwé Ààrẹ Babangida

Lekan Orenuga

134

Àwọn olókìkí ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà tí ṣètọrẹ sí ilè ìkàwé Ààrẹ tẹ́lẹ̀ rí Ibrahim Badamosi Babangida, láti wà ní Minna, Ìpínlẹ̀ Niger.

‎ Ọjọ́bọ̀ ní wọ́n ṣé ìfilọ́lẹ̀ ìwé Ààrẹ tẹ́lẹ̀ rí náà, ìtàn-àkọọlẹ tí Ààrẹ ológun tí wọ́n pé àkọlé rẹ̀ ní; Ìrìn-àjò kán nínú Iṣẹ́, onígbá méjì, èyí tí yóò ṣé ikowojọ fún Iṣẹ́ Ilè-ìkàwé Ààrẹ náà.

‎Àwọn ènìyàn jankan jankan àti àwọn olókìkí ọmọ Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ló ṣe agbatẹru àtìlẹ́yìn ẹbùn owó ìyìn náà.

‎ Alága àti Olùdásílẹ̀ BUA, Abdul Samad Rabiu, ló bẹ̀rẹ pẹ̀lú owó ẹbùn bílíọ̀nù márùn Náírà (₦5b), bí Gen. Theophilus Danjuma náà ṣé fí bílíọ̀nù mẹta náírà (₦3b) kún ẹbùn owó náà.

‎ Ọkùnrin ọlọlá jùlọ ní Áfíríkà, Aliko Dangote, ṣé ìlérí bílíọ̀nù mẹjọ Náírà (N8b) láàrín ọdún mẹrin tó mbọ̀.

‎ Àwọn owó ẹbùn pàtàkì mìíràn láti ọ̀dọ̀ Sẹnetọ̀ Sani Musa àádọtalélugba mílíọ̀nù Náírà (N250m) àti Mustapha Chike-Obi ṣé inawọsi méjì pèlú àádọ́ta mílíọ̀nù Náírà (N50m) láti ọ̀dọ̀ Bánkì ‘Fidelity’ àti ọgọrùn mílíọ̀nù mìíràn (N100m) láti ọwọ tirẹ̀.

‎ Ààrẹ Ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà, Godswill Akpabio, náà ṣèlérí àádọ́ta mílíọ̀nù Náírà (N50m), nígbà tí Ìgbákejì rẹ̀, Barau Jibrin, ṣèlérí ogún mílíọ̀nù Náírà (N20m)

‎ Sẹnetọ̀ Aliyu Wadada, tó sójú fún Ààrẹ Ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà náà, Alagba Godswill Akpabio àti Jibrin, ṣé àdéhùn mílíọ̀nù mẹ́wàá Náírà (N10m).

Comments are closed.

button