Take a fresh look at your lifestyle.

Nàìjíríà Sàtìlẹyìn Fún Super Eagles Síwájú Àsekágbá Eré Ìdárayá AFCON

158

Látàrí àsekágbá eré ìdárayá AFCON tí ìrètí wà pé yóò wáyé ní ọjọ́ Àìkú níbi tí ẹgbẹ́ agbábọ́ọ̀lù Super Eagles ti Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà yóò ti figa -gbága pẹ̀lú ojúgbà rẹ̀, Elephant ti Orílẹ̀-èdè Ivory Coast, ẹka ìfọ̀rọ̀léde Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ti pè fún àtìlẹyìn àwọn ọmọ Nàìjíríà

 

Mínísítà fún ìfọ̀rọ̀léde, Mohammed Idris se ìfiléde wípé ẹka ìlanilọ́yẹ̀ yóò pín àsìá pélébé-pélébé fún ọmọ Nàìjíríà fún ìsàfihàn àtìlẹyìn wọn

 

Idris wá rọ àwọn ọmọ Naijiria ti o wa ni Orilẹ-ede Ivory Coast lati tú yááyá lọ sí pápá eré ìdárayá, láti se kóríyá fún ẹgbẹ́ agbábọ́ọ̀lù Super Eagles

 

Comments are closed.

button