Ìgbákejì Ààrẹ Orílè-èdè Nàìjíríà, Kashim Shettima tí fí ìrètí rẹ̀ hàn pé Nàìjíríà yóò bóri àwọn ìṣòro tó ń kojú rẹ lọ́wọ́lọ́wọ́.
O ṣé ìkéde náà ní Beijing, China, ní ọjọ́ Ajé làkókò ìpàdé pẹ̀lú Aṣojú àti àwọn òṣìṣẹ́ tí Ilé-iṣẹ́ ilẹ̀ òkèèrè tí Nàìjíríà ní Ìlú China.
VP Shettima, tó wa ní Orílẹ̀-èdè China láti ṣé aṣojú Ààrẹ Bola Tinubu níbí ìpàdé ẹlẹẹkẹta ‘3rd Belt and Road Initiative,’ èyí tí Orílẹ̀-èdè China gbá àlejò rẹ̀, Ó ṣé àkíyèsí pé àwọn Adari Nàìjíríà ní àwọn ìmọ oyè gẹ́gẹ́ bí olórí tó tayọ ti a lè lò fún àpẹẹrẹ.
VP Shettima ṣàfikún pé “gbogbo òun tí a nilo ní láti ṣé àtìlẹ́yìn fún Ààrẹ Tinubu.”
Nígbàtí o n sọ̀rọ̀, aṣojú Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà sí China, Ahmad Jedda, sọ pé àbẹwò tí Ìgbákejì Ààrẹ sí China yóò ṣé ìrànlọ́wọ́ láti mú kí àsopọ Nàìjíríà àti China pọ̀ sí.
Leave a Reply