Take a fresh look at your lifestyle.

Ààrẹ Tinubu Dáwọ̀ọ́ Ìdùnnú Pẹ̀lú Gómìnà Tẹ́lẹ̀rí Fayẹmi Níbi Ayẹyẹ Ọjọ́ Ìbí Ọgọ́ta Ọdún

8

Ààrẹ Bọla Ahmed Tinubu ti dunnú pẹ̀lú gómìnà Ìpínlẹ̀ Ekiti tẹ́lẹ̀rí, Kayọde Fayẹmi níbi ayẹyẹ ọjọ́ ìbí ọgọ́ta ọdún rẹ̀, ó sàpèjúwe rẹ gẹ́gẹ́ bí olùfarajì, olóòótọ́ tí ó ń lo ìgbé ayé rẹ̀ fún ìgbáyégbádùn ọmọnìyàn

 

Nínú ìfọ̀rọ̀léde rẹ tí ó wáyé ní ọjọ́ Àìkú, Ààrẹ Tinubu gbósùbà fún Fayẹmi látàrí iṣẹ́ ribiribi tí ó ṣe gẹ́gẹ́ bi gómìnà ní ìpínlẹ̀ Ekiti tẹ́lẹ̀rí àti fun Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà lápapọ̀ àtipé ó se takuntakun fún ìsàfirinlẹ̀ ìjọba tiwa-n-tiwa tí ó wáyé ní ọdún 1999

 

Ó lu Fayẹmi lọ́gọ ẹnu fún àtìlẹyin tí ó se ati akitiyan rẹ síwájú, lásìkò ìpolongo ìbò, lásìkò ìdìbò sí ipò ààrẹ èyí tí ó mú kí òun jáwé olúborí nínú ìdìbò gbogbogbòò tí ó wáyé ní ọdún 2023

 

Ààrẹ wa gbàdúrà ẹ̀mí gígùn àti àlàáfíà tí ó péye fún gómìnà tẹ́lẹ̀rí náà

 

 

Comments are closed.

button