Take a fresh look at your lifestyle.

Mínísítà Jẹ́jẹ̀ẹ́ Láti Wá Ojútùú Sí Àwọn Ìpèníjà Tí Ó Ń Kojú Ẹka Ìkọ́lé

0 162

Mínísítà tí ó wà fún ìpèsè Ilé àti Ìdàgbàsókè Àgbègbè, Ahmed Musa Dangiwa ti jẹ́jẹ̀ẹ́ láti wá ọ̀nà àbáyọ sí àwọn ìsòro tí ó ń kojú ìpèsè ilé papàá jùlọ ìsòro àti wàhálà láti rí ilẹ̀ fún ilé kíkọ́.

 

Mínísítà sọ ọ̀rọ̀ náà nígbà tí ó ń se ìpàdé pẹ̀lú alága ìgbìmọ̀ ìsàtúnṣe ilẹ̀, Ọ̀jọ̀gbọ́n Peter O. Adeniyi àti àwọn ẹmẹ̀wà rẹ̀, Ó sàlàyé pé ètò ti parí láti wá ọ̀nà àbáyọ bí ilẹ̀ ìkọ́lé yóò se wà fún lílò ní Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.

 

Dangiwa jẹ́jẹ̀ẹ́ àtìlẹyìn ààrẹ Bọla Ahmed Tinubu fún àseyọrí ìgbìmọ̀ náà, Ó wá lùwọ́n lọ́gọ ẹnu fún iṣẹ́ ribiribi ti wọn se.

 

 

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

button