Ìgbéjọ́ lórí ayédèrú òògùn ikọ́ tí ó sekúpa àwọn ọmọdé ní ọdún tí ó kọjá ní Orílẹ̀-èdè Gambia ti bẹ̀rẹ̀, ní Ilé Ẹjọ́ Gíga tí ó fi Banjul se ibùjókòó
Àwọn ìdílé tí ọ̀rọ̀ kàn ń retí ìdájọ́ òdodo lẹ́yìn ìgbẹ́jọ́ náà èyí tí ó yẹ kí ó ti wáyé láti inú osù keje sùgbọ́n tí wọ́n sún síwájú di osù kẹwàá nígbà tí àwọn tí wọ́n fi ẹ̀sùn kàn kùnà láti yọjú sí ilé ẹjọ́.
Àwọn ọmọdé tí òǹkà wọn tó àádọ́rin ni ó pàdánú ẹ̀mí wọn ní ọdún 2022 nígbà tí kídìnrín wọn daṣẹ́-sílẹ̀ lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n lo ayédèrú òògùn náà.
Leave a Reply