Ẹ Jẹ́ Kí Èdè Lárúbáwá Di Ohun Àmúlò Ní Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà- Ọ̀jọ̀gbọ́n Fásitì Kan Pàrọwà
Wọ́n ti pàrọwà sí ìjọba àpapọ̀ láti jẹ́ kí èdè lárúbáwá di ohun àmúlò ní Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.
Alákòóso ìtẹ̀síwájú nípa ètò ẹ̀kọ́ tí Fásitì Ìpínlẹ̀ Kwara (KWASU), Mọlete, Ọjọgbọn Hamzat Abdulraheem ni ó pe ìpè náà ní ìlú Ilorin, Ìpínlẹ̀ Kwara, Ààrín gbìngbìn Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.
Ó sàfirinlẹ̀ pé, èdè Larúbáwá ni èdè àmúlò àti èdè ẹ̀sìn tẹ́lẹ̀rí kí àwọn òyìnbó tó wọlé sí Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Ó wá pàrọwà fún àdápadà èdè náà fún ànfààní àwọn akẹ́kọ̀ọ́ tí ó fẹ́ tẹ̀síwájú nínú ẹ̀kọ́ wọn pẹ̀lú èdè Lárúbáwá.
Leave a Reply