Mínísítà Fún Ìdàgbàsókè Àwọn Ọ̀dọ́, Jamila Biọ Ibrahim ti kí Emir Ìlú Ilọrin, Alayélúwà Alhaji Ibrahim Sulu Gambari kú oríire ayẹyẹ ọdún méjìdínlọ́gbọ̀n lórí àpèrè
Alákòóso ìfọ̀rọ̀léde fún Mínísítà, Maryam Yusuf ni ó fi ọ̀rọ̀ náà léde
Sulu Gambari dé orí àpèrè gẹ́gẹ́ bí Emir ẹlẹ́ẹ̀kọkànlá ní ọjọ́ kejìdínlọ́gbọ̀n osù kẹjọ ọdún 1995, Ó sì wé láwàní ní ọjọ́ kọkànlá osù kọkànlá, ọdún 1995 nígbà tí ó kọ̀wé fi ipò rẹ̀ sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí adájọ́ ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn, ní ìlú Èkó
Ó sàpèjúwe ọba alayé náà gẹ́gẹ́ bí adarí rere tí ìdàgbàsókè ìlú sì jẹ ẹ́ lógún
Leave a Reply