Mímú Ìgbòòrò Bá Ètò Ẹ̀kọ́ Se Pàtàkí Fún Ìdàgbàsókè Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà- Alákòóso Ilé Akéde
Alákòóso Ilé Akéde Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, Mallam Jibrin Baba Ndace ti jẹ́jẹ̀ẹ́ àtìlẹyìn rẹ̀ láti mú ìdàgbàsóke bá ètò ẹ̀kọ́ ní Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà
Ó sọ ọ̀rọ̀ náà nígbà tí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ilé ìwé ìmọ̀ ẹ̀rọ tí ó wá ní Akwanga, Ìpínlẹ̀ Nasarawa se àbẹ̀wo sí ọ́ọ́fìsì rẹ̀ ní ìlú Abuja
Alákòóso àgbà náà fi àrídájú hàn sí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ wípe, ilé akéde ń se àtìlẹyìn fún ètò ẹ̀kọ́, ní pàtàkì, láàrin àwọn ológun nílé àti ní òkè òkun. Ó gba àwọn akẹ́kọ̀ọ́ náà níyànjú láti di akọ̀ròyìn ní ọjọ́ iwájú fún ìdàgbàsókè àwùjọ.
Leave a Reply