Ààrùn covid ti di ẹgbàáta- lé- ní- ọ̀kẹ́- mẹ̀wáá- ó- lé- ní- èjì- dín -–lọ́gọ́je ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà
Eyitayọ Fauziat Oyetunji
Ilé-iṣẹ́ tó ń mójútó àjàkálẹ̀ ààrùn ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà (NCDC ) ṣọ pé,ààrùn ọ̀hún ń pọ̀ si ni lójoojúmọ́,ènìyàn mẹ́rìnlé-láàdọ́rin miràn ló tún ti kó ààrùn náà ní ọjọ́ àìkú.
Ajọ naa sọ pe ,lọwọlọwọ bayii eniyan ẹgbaata-le-ni-ọkẹ-mẹwa-o-le-ni-eji-din-logoje lo ti ni aarun naa,ti a ba fi mẹrinle-laadọrin to ṣẹṣẹ ko mọ tilẹ tẹlẹ.
Ajọ ọhun sọ pe,awọn eniyan to ṣẹṣẹ ko aarun naa jẹyọ ni awọn ipinlẹ mẹsan-Lagos (mẹrindin-logoji ),Edo (mọkanla ), Olu-ilu (mẹsan ), Akwa Ibom (mẹfa ), Sokoto (mẹfa), Delta (mẹta ),Benue (ẹyọkan),Ọyọ (ẹyọkan), Rivers State (ẹyọkan).
Ọ sọ pe, eniyan ẹgbaata-le-ni-ọkẹ-mẹwa-o-le-ni-eji-din-logoje lo ti ko aarun naa,eniyan ẹgbàájì –le- ni- ọ̀kẹ́- mẹ̀sán- abo- o- le –ni- ẹ̀ta- din- lọgọ́rùn ti gba iwosan, ti ẹ̀ta-le-ni-okòó- le- lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ́ẹ̀rinlá si ti jẹpe oluwa ni ipinlẹ mẹrindin-logoji ati olu-ilu.
Leave a Reply