Take a fresh look at your lifestyle.

Ìgbákejì Ààrẹ Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà Pé Fún Àlàáfíà, Ìfarádà Òṣèlú Ní Ìpínlẹ̀ Kano ‎

Lekan Orenuga

76

Ìgbákejì Ààrẹ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, Kashim Shettima tí ké sí àwọn Olóṣèlú ní ìpínlẹ̀ Kano, Ìwọ̀-oòrùn Àríwá Nàìjíríà láti gbá àlàáfíà láàyè kó jọba ní Ìpínlẹ̀ náà.

‎ Shettima ṣé ìpè yìí l’àkókò tó ṣé àbẹwò ìtùnú sí ìdílé Galadinma Kano, Alhaji Abbas Sanusi, tó kú láìpẹ́ yìí.

‎ Ìgbákejì Ààrẹ náà sọ pé òún rọ́ àwọn olóṣèlú náà láti má jẹ́ kí òṣèlú ẹlẹyamẹya pín wọ́n yẹlẹ-yẹlẹ, Ó sọ́ èyí ní ilé olóògbé náà.

‎ Ó sàlàyé pé “ Ìpínlẹ̀ Kano ní ọkàn àríwá tí òún sí wá láti Àríwá náà”, Ó wá ń gbá làdúrà pé, “Kí Ọlọ́run Allah mú ìsọkan wà láàárín wà.”

‎ Nígbà tó n sọrọ tẹlẹ, Gómìnà Ìpínlẹ̀ Kano, Abba Kabir Yusuf dúpẹ lọ́wọ́ Ìgbákejì Ààrẹ lórúko ìjọba ìpínlẹ̀ náà àti àwọn ènìyàn Ìpínlẹ̀ Kano.

Comments are closed.

button