Ìgbákejì Ààrẹ Ilé-ìgbìmọ̀ Aṣòfin Àgbà Yóò Ṣé Ònígbọwọ́ Awọ́n Ọ́ọ̀dúnrún Ní Ilé-Ẹ̀kọ́ Gíga
Lekan Orenuga
Ìgbákejì Ààrẹ Ilé-ìgbìmọ̀ Aṣòfin Agba, Barau Jibril, tí ṣé ìfilọ́lẹ̀ ètò ilé-ẹ̀kọ́ fún àwọn Ọ́ọ̀dúnrún ọmọ abínibí Ìpínlẹ̀ Kano sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ilé-ẹ̀kọ́ gíga Nàìjíríà lábẹ́ àbójútó “Barau Jibril Foundation.”
O sọ pé sikọlaṣipu náà ní yóò ṣé ìgbà láàyè fún àwọn tó fẹ́ kọ́ nípa Ìmọ Ẹrọ AI, Ọgbìn, Àyíká, àtí ìkọ́ni-lẹ́kọ̀ọ́.
Sẹnetọ Barau sàlàyé pé àwọn ilé-ẹ̀kọ́ gíga Nàìjíríà tí a yan ní Ilé-ẹ̀kọ́ gíga Obafemi Awolowo Ile-Ife, Ìpínlẹ̀ Ọsun, Ilé-ẹ̀kọ́ gíga tí Ìbàdàn, ìpínlẹ̀ Ọyọ, Ilé-ẹ̀kọ́ gíga Ahmadu Bello, ìpínlẹ̀ Kaduna àti Fasiti Bayero, ìpínlẹ̀ Kano.