Ààrẹ Nàìjíríà tẹ́lẹ̀ rí, Jonathan ṣàpèjúwe olóògbé Dokpesi gẹ́gẹ́ bí olùṣòwò aláànú
Eyitayọ Fauziat Oyetunji
Ààrẹ Nàìjíríà tẹ́lẹ̀ rí, Goodluck Jonathan, ti banújẹ́ lórí ikú olùdásílẹ̀ DAAR Communications, Olóyè àgbà Raymond Dokpesi.
Nínú ìfiránṣẹ́ ìkẹ́dùn kan, Jonathan sọ pé Nàìjíríà ti pàdánù olólùfẹ́ orílẹ̀-èdè rẹ̀ lódodo àti ẹni tó ní ọkàn tó mọ́.
Jonathan, ẹni tí ó jẹ́ ọ̀kan lára àwọn abánikẹ́dùn tó kọ́kọ́ ṣàbẹ̀wò sí ilé Dokpesi ní Àbújá, ní ọjọ́ Ajé,ó ní òun bá Dokpesi ṣe ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́.
“A ó máa ṣèrántí rẹ̀ fún iṣé ọrẹ,ìgbàgbọ́ àti ìṣàkóso tó wúnilórí pàápàá jùlọ olùfilọ́lẹ̀ tí ó bẹ̀rẹ̀ ìgbohùn sáfẹ́fẹ́ aládàáni, tí ó sí kó ipa pàtàkì nínú ìdàgbàsókè òmìnira àwọn oníròyìn ní Nàìjíríà.,” ó sọ báyìí.
Dókítà Dokpesi di olóògbé ní ọjọ́ Ajé,ní ọmọ ọdún mọ́kànlé-láàdọ́rin.
Leave a Reply