Asojú orílẹ̀ èdè France àti Germany tí ó wà ní orílẹ̀ èdè Ethopia ti fi léde pé, àsọyépọ̀ kò le è wáyé láì fi ìdájọ́ òdodo rinlẹ̀ láàrin àwọn tí ọ̀rọ̀ kàn ní orílẹ̀ èdè náà.
Wọ́n sọ̀rọ̀ ní ìlú Addis Ababa lẹ́yìn ìpàdé pẹ̀lú Mínísítà Abiy Ahmed lórí ìtẹ̀síwájú nípa àdéhùn àlàáfíà tí ó wáyé nínú osù kọkánlá láàrin ìjọba àpapọ̀ orílẹ̀ èdè Ethopia àti àwọn ọmọ ogun ọlọ̀tẹ̀ Tigrayan.
Ìjọba Amẹ́ríkà náà sàlàyé pé àlàáfíà ti ń jọba ní àgbègbè náà, nígbà tí àwọn tí ọ̀rọ̀ kàn fi àrídájú hàn pé, ẹlẹ́ṣẹ̀ kan kò ní lọ láì jìyà.
Leave a Reply