Take a fresh look at your lifestyle.
Election

Nàìjíríà Daro Ikú Gbajúgbajà Àgbábọ́ọ̀lù Pele

0 149

Ààrẹ Muhammadu Buhari tí dára pọ̀ mọ́ àwọn aṣáájú àgbáyé láti fi ìbànújẹ́ hàn lórí ikú gbajúgbajà agbabọ́ọ̀lù Brazil, Edson Arantes do Nascimento, tí a mọ̀ sí Pele tó kú ní ọjọ́bọ̀.

Àgbábọ́ọ̀lù afẹsẹgba tó tóbi jùlọ́ ní àgbáyé tí kù lẹyìn tó já ìjàkadì pẹ̀lú àrùn Kansa.

Pele, ẹní tó gbà ife Àgbáyé mẹ́ta làkókò tó ń gbà bọ́ọ̀lù ṣoju orílẹ̀-èdè Brazil tó sì gbà bọ́ọ̀lù wọlé ní ìgbà ẹgbẹ̀rún lé ní ìgbá àtí díẹ̀ (1,281). Ní ọdún 2000 ló gbà ìsàmì àgbábọ́ọ̀lù tó peregede jùlọ́.

Ní orí ìyìn fún gbajúgbajà àgbábọ́ọ̀lù náà lórúkọ gbogbo ọmọ Nàìjíríà, Ààrẹ Buhari sọ pé “Kó sún ùn rè.” “O ṣé ayé rè, O sí sá àpá rẹ̀ fún ìdàgbàsókè bọ́ọ̀lù àgbáyé àti gbogbo èrè ìdárayá lágbáyé.

“O ní onínúure àti òníwà pẹlẹ ní àgbábọ́ọ̀lù náà láìbikita sí àṣeyọrí rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí eléré ìdárayá tó fá akọyọ jù. Kò sí ṣé ìyapa láàrín orílẹ̀-èdè, ẹ̀yà tàbí ẹsìn. Ó tún jẹ́ aṣojú onínúure fún àjọ United Nations.”

“Pele tí lọ́ ṣùgbọ́n a kò ní gbàgbé rẹ̀. Sún ùn rè o!”

Lekan Orenuga

Leave A Reply

Your email address will not be published.