Ààrẹ Buhari ti orílẹ̀ èdè Nàìjíríà ti ṣe ìfilọ́lẹ̀ ìpìlẹ̀ ọ́ọ́fìsì àpapọ̀ àjọ ECOWAS ní ìlú Abuja, olú ìlú orílẹ̀ èdè Nàìjíríà.
Ààrẹ, ẹni tí ààrẹ Umaro Embalo ti orílẹ̀ èdè Guinea Bussau ati ààrẹ Julius Mada Bio ti orílẹ̀ èdè Sierra Leone kọwọrin pẹ̀lú rẹ̀ sọ wipe, píparí gbọ̀ngàn náà yóò mú ìsọ̀kan ba àjọ ECOWAS.
Ìjọba orílẹ̀ èdè China ni ó fi gbọ̀ngàn náà ta àjọ ECOWAS lọ́rẹ, ti wọn yóò sì máa pè é ní “Àmúyẹ ìwọ̀ oòrùn Africa” ( Eye of West Africa). Ìrètí wà pé isé náà yóò parí ní osù kejì ọdún 2025 ( February, 2025).
Leave a Reply