Gómìnà ìpínlẹ̀ Niger kẹ́dùn pẹ̀lú àwọn tó fara káàsá ìjàǹbá ọkọ̀ ojú omi
Eyitayọ Fauziat Oyetunji
Gómìnà Abubakar Sani Bello ìpìnlẹ̀ Niger ní arinwá-àárín Nàìjíríà ti kẹ́dùn pẹ̀lú àwọn ènìyàn Lavun àti àwọn agbègbè ìjọba Mokwa lórí Ìjàǹbá ọkọ̀ ojú omi tí ó yọrí sí pípádánù ẹ̀mí.
Gomina ninu ọrọ rẹ kan lati ọdọ agbẹnusọ rẹ ni ọjọ Abamẹta, Mary Noel Berje, ṣe apejuwe iṣẹlẹ naa gẹgẹ bi ajalu ati aburu.
O wa dupẹ lọwọ ile-iṣẹ to n risi pajawiri ni ipinlẹ Niger, (NSEMA) ati awọn ọmọ ẹgbẹ agbegbe omi fun ipa wọn ninu iṣẹ wiwa ati fun igbala awọn olufaragba.
Bi o ṣe n kẹdun pẹlu awọn ẹbi awọn to padanu ẹmi wọn, gomina ipinlẹ Niger ti paṣẹ fun awọn ile-iṣẹ to je mọ nnkan bẹyẹn lati gbe awọn igbesẹ to ṣe pataki lati yago fun iru ijanba bẹẹ nigba miran.
Leave a Reply