Olórí orílẹ̀ èdè Mali Col. Assimi Goita tí ó jẹ́ alákóso ètò ìjoba fún ọdún méjì gbáko, lẹ́yìn tí ó ti di ọ̀tẹ̀ gba ìjọba, ti dá ìwọ́ ìdùnnú pẹ̀lú àwọn ará ìlú fún ayẹyẹ ọdún méjìlélọ́gọ́ta irú rẹ̀ tí wọ́n gba òmìnira kúrò lọ́wọ́ ìjọba amúnisìn. Ètò náà wáyé ní olú ìlú náà tíí se Bamako.
Orílẹ̀ èdè Mali ti ń da ojú kọ dídá ẹyẹ sí láti ọ̀dọ̀ orílẹ̀ èdè àgbáyé látàrí ìdìtẹ̀ gba ìjọba àti kíkùnà gbèdéke ìjọba àgbáyé lórí àsìkò láti se ètò ìdìbò yan olórí titun.
Orílẹ̀ èdè Farasé tí ó ti fi ìgbà kan kó ogun ja àwọn alákatakítí ̀ẹ̀sìn fún ọdún mẹ́sà án ní orílẹ̀ èdè Mali ti kó àwọn ọmọ ogun kúrò, léyìi ́tí ó fún orílẹ̀ èdè náà ní ìsèjọba tiwa n tiwa tí ó péye.
Leave a Reply