Nottingham Forest ti jẹrí ṣí Ìfarapa Emmanuel Dennis ògbóntarìgì agbábọ́ọ̀lù ọmọ Nàìjíríà tó yẹ kó gbá bóòlù pẹ̀lú orílè-èdè Algeria ní ọ̀sẹ̀ tóńbọ̀ nínú ìdíje ọlọ́ọ̀rẹ́sọ̀rẹ́ sùgbón wón ti fi agbábọ́ọ̀lù Gift Saviour rọ́pò rẹ̀ báyìí.
Àwọn olólùfẹ̀ eré bóòlù sọ wípé irọ́ ni agbábọ́ọ̀lù náà n pa, kòfẹ́ kópa fún orílẹ̀-èdè rẹ̀ ni, ẹgbẹ́ agbábọ́ọ̀lù Forest wá ko yọ wípé kòríbẹ̀. Nínú ìwé àtẹ̀jáde ránpẹ́ tí wọn kọ, wọn sọ pé wón ti pe Taiwo Awoniyi fún ìdíje náà tí yóò wáyé ní ọjó Ajé, ọjó kẹtàdínlọ́gbọ̀n, ní aago mẹ́jọ lálẹ́ ti àkókò ti ilẹ̀ UK.
Dennis ẹni tí wọ́n ní kí o wá sojú fún ẹni tó ní ipalara-Henry Onyekuru sùgbón tí ó yani lẹ́nu nítorí òun náà ti ní Ìfarapa.
Tèmítọ́pẹ́ Òbísẹ̀san
Leave a Reply