Take a fresh look at your lifestyle.

Ìgbéyàwó Ẹ̀yà kan Sí Òmíràn Máa Ń Fa Ìsọ̀kan

0 246

Agbẹnusọ ilé ìgbìmọ̀ asòfin Ìpínẹ̀ Nasárawa, Balarabe Abdullahi ti gba àwọn ọmọ Nàìjíríà ní ìyànjú pé, fífẹ́ ara ẹni láti inú ẹ̀yà kan sí òmíràn máa ń fa ìbágbépọ̀ àlàáfíà àtipé ó ń mú ìsọ̀kan orílẹ èdè wa dúró sinsin.

 

Abdullahi fi ọ̀rọ̀ náà léde níbi ayẹyẹ ìgbeyàwó asojú ọmọ ẹgbẹ́  tí ó pọ̀ jùlọ ní ilé ìgbìmọ̀ asòfin ìpínlẹ̀ Benue, léyìí tí ìdàpọ̀ mímọ́ náà wáyé láàrin àwọn ènìyàn ìpínlẹ̀ Nasarawa àti Benue.

 

Àrọwà náà se pàtàkì papàá jùlọ ní àsìkò tí orílẹ̀ èdè Nàìjíríà wà nínú ìdààmú wàhálà ẹlẹ́yà mẹ̀yà, èto àbò tí kò péye, tí ìpàniyan si gba ile gba oko.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

button