Ìkọlù Ńlá tó sẹlẹ̀ ní Shiroro,ìpínlẹ̀ Niger jẹ́ èyí tó tani lára púpọ̀ – Ààrẹ Buhari.
Ọlórí Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, Ààrẹ Muhammadu Buhari ṣe àpèjúwe ìkọlù tó wáyé ní ọjọ́bọ̀ ní Shiroro, Ìpínlẹ̀ Niger gẹ́gẹ́ bíi èyí tí ó burú jáì
Ààrẹ bá àwọn ará ìlú shiroro kẹ́dùn, ó sì gbóríyìn fún àwọn ọmọ ọlọ́gun Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà fún ìwà akíkanjú àti ìfarajìn wọn fún ààbò ìlú
Ó wá ṣe àfikún rẹ̀ pé, Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà yóò tẹ̀síwájú lóóri gbígbógun ti ìwà awọn oníṣé láabi àti ìwà jàndùkú lórílẹ̀-èdè Nàìjíríà, àti wípé ẹlẹ́ṣẹ̀ kan ò le è lọ láí jìyà.
Ọláyinká Akíntọ́lá.
Leave a Reply