Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà àti Portugal buwọ́lu ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìwé ìrántí òye fún ìfọwọ́sowọ́pọ̀ ní àwọn apá oríṣiríṣi ní ọjọ́ Jímọ̀ ní Lisbon.
Ayeye ìbuwọ́lù náà jẹ́ nípasẹ̀ àwọn oṣiṣẹ ìpele mínísítà láti orílẹ̀-èdè méjèèjì gẹ́gẹ́ bíi ara Ìbẹ̀wò Ìpínlẹ̀ tí Ààrẹ Muhammadu Buhari lọ ṣe ní orílẹ̀-èdè European lápapọ̀.
Ààrẹ Buhari àti olórí ìjọba ilẹ̀ Portugal, Antonio Costa jẹ́ ẹlẹ́ẹ̀rí ayẹyẹ ìbowọ́lù náà.
Ọláyinká Akíntọ́lá.
Leave a Reply