Ààrẹ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, Muhammadu Buhari yóò pàdé Ààrẹ United Arab Emirates (UAE) titun, Sheikh Mohamed bin Zayed Al Nahyan, láti sọ̀fọ̀ ikú Ààrẹ àná àti alákóso Abu Dhabi, Sheikh Khalifa bin Zayed Al Nahyan.
Ààrẹ Buhari, tí yóò kúrò ní Abuja ní Ọjọ́bọ̀ yóò tún ṣe ìkíni rẹ̀ sí Ààrẹ titun. Yóò si fi àkókò náà se àtẹnumọ́ àdéhun pípẹ́ tí ó wà láàrín Nàìjíríà àti UAE.
Leave a Reply