ASUP:Ilé-èkọ́ gíga iṣẹ́ ọwọ́ Násáráwá Darapọ̀ mọ́ ìyanṣẹlódì gbogbogbòò
Eyitayọ Fauziat Oyetunji
Ẹgbẹ́ òṣìṣẹ́ olùkọ́ni ilé-ẹ̀kọ́ gíga iṣẹ́-ọwọ (ASUP), Isa Mustapha Agwai, Láfíà, ìpínlẹ̀ Násáráwá, Nàìjíríà ti darapọ̀ mọ́ ìkìlọ̀ ìdaṣẹ́sílẹ̀ ọlọ́sẹ̀ méjì tí ẹgbẹ́ náà kéde jákèjádò orílẹ̀-èdè lórí bíbèèrè fún ìgbé ayé ìrọ̀rùn àwọn ọmọ ẹgbẹ́.
Alaga ẹgbẹ ile-ẹkọ naa, Ọgbẹni Silvester Aku, lo sọrọ naa lasiko to n ba awọn oniroyin sọrọ ni Lafia, olu-ilu ipinlẹ naa.
Gẹgẹ bi o ti sọ, idaṣẹsilẹ naa wa ni ibamu pẹlu aṣẹ lati olu ile-iṣẹ wọn lori ipinnu ti o waye nibi ipade Igbimọ Alaṣẹ apapọ ẹgbẹ ti o waye ni ilu Abuja.
Ọgbẹni Aku sọ pe igbese naa ti o di eyi ti ko ṣee yẹ,waye nitori ikuna Ijọba apapọ lati ṣe awọn nnkan ti wọn beere gẹgẹ bi o ṣe wa ninu iwe adehun ti o fowo si ni ọdun 2021.
Leave a Reply