Ààrẹ Muhammadu Buhari sọ pé ikú Ààrẹ orílẹ̀-èdè United Arab Emirates (UAE) Sheikh Khalifa Bin Zayed Al Nahyan ti jayé lólè ọ̀kan lára àwọn aṣáájú tó wúni lórí jù lọ lákòókò yìí.
Ilé-iṣẹ́ Ìjọba ti UAE ti kéde pé wọn yóò fi ogójì ọjọ́ ṣe ìdárò tí àṣìà orílẹ̀-èdè yóò wà ní ìdajì àti títi àwọn ilé-iṣẹ́ àjọ, ilé-iṣẹ́ òṣìṣẹ́ àpapọ̀, ìpele agbègbè àti ti aládàáni fún ọjọ́ mẹ́ta
Olóògbé tí a bí ní ọdún 1948, kò fibẹ́ẹ̀ jáde síta láti ìgbà tí ó ti ní ìkọlù àìlegbàpágbẹ́sẹ̀ ní ọdún 2014, arákùnrin rẹ̀, Abu Dhabi ọmọọba Mohammed bin Zayed, ni a ti rí bíi adarí UAE ní àwọn ọdún díè sẹ́yìn.
Ọláyinká Akíntọ́lá
Leave a Reply