Gómìnà ìpínlẹ̀ Kánò ní iwọ̀ oòrùn àríwá orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, Ọ̀mọ̀wé Umar Ganduje ti fọwọ́sí i fún igbákejì rẹ̀ Dókítà Nasiru Yusuf Gawuna, gẹ́gẹ́ bí olùdíje ipò gómìnà fún ẹgbẹ́ òṣèlú All Progressives Congress ní ìpínlẹ̀ ńàa.
Kọmisana fun ijọba ibilẹ ati ọrọ-ọba ti o ṣẹṣẹ kuro, Murtala Sule Garo tun fọwọsi Gawuna gẹgẹ bi oludije, fun idibo gbogbogbo 2023 ti n bọ ni ilu iṣowo atijọ Kano.
O so eyi di mimọ lasiko ipade awọn agbẹnusọ ẹgbẹ oselu All Progressives Congress (APC) ni ipinlẹ na, to waye ni Africa House,ile-iṣẹ ijọba,ni ilu Kano.
O ni awọn ṣe ipinnu naa nigba ti won ti fohunsọkan lẹyin ifọrọwanilẹnuwo lọpọlọpọ pẹlu gbogbo awon gboogi ẹgbẹ naa,o tun sọ siwaju pe gbogbo ilana ẹgbẹ ni wọn ti tẹle ki wọn too ṣe ipinnu ọhun.
Leave a Reply