Take a fresh look at your lifestyle.

Al-Shabaab sọ pé òun ló wà nídìí ìkọlù apànìyàn tó ṣẹlẹ̀ ní Ibùdó AU ní Sòmálíà

Eyitayọ Fauziat Oyetunji

0 245

Àwọn ajagun Al-Shabaab ti yabo ilé-iṣẹ́ ìṣọ̀kan Áfíríkà kan ní Sòmálíà pẹ̀lú ìbọn àti ibẹjadi ní ọjọ́ ìṣégun,ní èyí  tí ó fa ìyìnbọn lura tí ó pa àwọn olùpèsè alààfíà Burundi.

Ọgágun ọmọ ogun Burundi kan ti o ga julọ sọ pe ọgbọn  ọmọ ogun ni wọn pa ti awọn mejile-logun miiran si farapa,nigba ti ọpọlọpọ si sọnu.

Eleyi jẹ ikọlu akọkọ  iru ẹ lori ibudo alafia lati igba ti AU Transition Mission ni Somalia (ATMIS) ti rọpo ologun ti tẹlẹ AMISOM ni ọjọ kinni, Oṣu Kẹrin.

Al-Shabaab, ti o ti n paniyan ni  ijọba aringbungbun  Somalia fun bii ọdun mẹwa kan sẹyin, sọ pe o ti gba iṣakoso  ibudó naa ati  pe oun ti pa awọn ọmọ ogun mẹ̀ta ĺe ńi àádọ́sán.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

button