Ààrẹ Muhammadu Buhari ti kan sáárá sí àwọn obìnrin Nàìjíríà lórí ayẹyẹ ọjọ́ àwọn obìnrin ágbàyè, tí wọ́n ń ṣe káàkiri àgbáyé ní Oṣù Kẹta ọjọ́ kẹjọ.
Ayẹyẹ náà ti wọ́n fún ní àkòrí “Gender Equality Today for a Sustainable Tomorrow,” ni Ààrẹ sọ pé ó jẹ́ àǹfàní láti ronú lórí àwọn ipá pàtàkì tí àwọn obìnrin gbé ṣe ní àwùjọ, ilé, ìṣàkóso ìjọba àti ní gbogbo ibi tí wọ́n ti bá ara wọn
Ààrẹ Buhari ṣàkíyèsí pé àwọn obìnrin jìnà sí ibi tí o yẹ ki wọn wa, ṣùgbọ́n ó gbàgbọ́ pé wọn kò lè fi ohun-ko-hun dù wọ́n fún ìgbà pípẹ́ mọ́, latari bí wọ́n ṣe ń fi hàn pé àwọn lè da duro ni gbogbo ọna
Leave a Reply