Ẹ̀ka tó ń bójútó àjálù àti ewu lórílẹ̀-èdè Nàìjíríà sọ pé gbogbo ènìyàn ló ní isé láti rè wipé ìjàm̀bá, ewu àti àjálù díkùn láwùjọ wa.
Minista fun ewu ati ajalu,Sadiya Umar Farouq lo sọ eyi ni Abuja.
O so pe “gbogbo eniyan lo ni ipa lati ko ninu idinku eewu ati ajalu. Gbogbo ajalu bẹrẹ ni agbegbe kan ṣaaju ki o to tan ka orilẹ-ede ati ti kari aye. Wo ọran ti Covid-19, o bẹrẹ lati Wuhan. Ko si ẹnikan ti o mọ Wuhan ṣaaju igbayi, ṣugbọn o tan kakari orile ede China ati kari aye”
Farouq tẹnumọ pe idasile eka yii ti fihan pe Naijiria ko ni oṣiṣẹ ti o to lati dena ajalu ni orilẹ-ede naa, nitori naa o ṣe pataki lati gbe awọn eto to ni itumọ kalẹ lati le din ewu ati ajalu ku.
Tolulọpẹ Akinṣẹyẹ
Leave a Reply