Ààrẹ orílẹ̀-èdè Nàijìríà, Muhammadu Buhari sọ pé ètò ọrọ̀-ajé Nàijìríà wà ní pípé, ó sì dáńtọ́.
Aarẹ tẹsiwaju, o sọ pe, awọn ohun ameyedẹrun to le ṣe ọrọ-aje Naijiria láǹfààní ti wa nilẹ; ni eyi ti yoo jẹ ki eto oro-aje Naijiria gbounjẹ fẹgbẹ-gbawobọ. Paapaa julo ẹrọ ayelujara, eyi ti o jẹ gbòńgì; ti yoo jẹ ki gbogbo orilẹ-ede agbaye miran le dara pọ mọ orilẹ-ede Naijiria lori eto ọrọ aje.
Ninu atẹjade kan to towọ aarẹ jade, aarẹ sọ pe awọn o sinmi lati jẹ ki ọrọ-aje Naijiria figa-gbaga pelu orile-ede agbaye yooku. Nitori pe, eyi yoo mu ki idokowo burẹkẹ si, ti yoo si fa ilọsiwaju ba ilu Naijiria
Akinseye Tolulope Henry
Leave a Reply