Anambra: Ẹgbẹ́ bẹnu àté lu bíí Àwọn abarapáá kò ṣe láǹfààní láti dìbò
Eyitayọ Fauziat Oyetunji
Ẹgbẹ́ àwọn olùwòye ìdìbò ti bẹnu àtẹ́ lu bí ìdá mẹ́rìnlé-láàdọ́ta nínú àwọn ọ̀nà tí ó lọ sí àwọn ààyè ìdìbò tí wọ́n ṣe àyẹ̀wò rẹ̀ fún Àwọn abara páá (PWDs) lákòókò ìdìbò gómìnà ní ọjọ àbámẹ́ta tó kọjá ní ìpínlẹ̀ Anambra kò ṣeé lọ.
Ẹgbẹ naa, “The Access Nigeria: Disability Votes Matter Campaign” tun ya wọn lẹnu bi Igbimọ idibo olominira orile-ede , (INEC) ko ṣe lagbara lati pese agbegbe ti o dara fun ikopa ti o munadoko fun awọn abarapaa PWDs.
Lakoko ti o n ba awọn oniroyin sọrọ lẹyin Idibo lori iṣayẹwo iraye si ibi-idibo lori idibo naa, Alakoso oludari,Inclusive Friends Association , olupilẹṣẹ Ipolongo Access Nigeria, Grace Jerry,ṣafihan binu rẹ ko ṣe dun lori bii igbimọ idibo ṣe fọwọ hẹ ẹtọ awọn PWDs lati kopa ninu idibo ọhun.
O sọ lafikun lati awọn apa idibo ti wọn ṣe ayẹwo rẹ pe, awọn oludibo abarapaa ni italaya lati wọle si ibi ti awọn apoti idibo wa,paapaa julọ awọn ti o n lo kẹẹkẹẹ ati aisi iwe idibo fun awọn afọju.
Alakoso Eto Ẹgbẹ naa, Moses Oluwasheyi, rọ INEC lati mu idanilẹkọ awọn oṣiṣẹ deede ati oṣiṣẹ onigba diẹ lati ṣakoso awọn ohun elo to munadoko fun oludibo pẹlu awọn alaabo.
Leave a Reply