Aarẹ orilẹ ede Naijiria,Muhammadu Buhari ti rọ awọn oludari Ogoni to wa ni ẹkùn Niger-Delta lati tubọ maa rọ awọn eniyan lati maa daabobo awọn ohun ìnì bii ọ̀pá epo rọbi ati awọn ti wọn lo lati pọn epo rọbi ni orilẹ ede yii.
Aarẹ Buhari tun wa rọ wọn lati dẹkun nipa bíba awọn ohun elo epo rọbi jẹ́ , nitori eyi lee fa idena eto idagbasoke ní ẹkun naa.
Aarẹ sọrọ yii lasiko to n tẹwọgba awọn oludari ilu Ogoni ni ẹkun Niger-Delta lọjọ Ẹti nile aarẹ to wa niluu Abuja.
Aarẹ Buhari ni ijọba ti setan lati se atunse si ilu Ogoni ati lati mu tẹsiwaju ninu eto idagbasoke ilu naa., ki awọn eniyan ilu naa lee padi si isẹ agbẹ wọn.
Ninu ọrọ rẹ, aarẹ igbimọ awọn lọba-lọba ti Ogoni , ọba Godwin Giniwa, wa dupẹ lọwọ aarẹ Buhari fun eto idagbasoke ti ijọba rẹ dawọle ni awọn ayika ti epo rọbi ti bàjẹ́.
Awọn ọba naa tun tẹsiwaju pe awọn fẹ́ ki isọkan orilẹ ede Naijiria tun tẹsiwaju nitori pe , nipa eyi ni ọjọ́ iwaju rere awọn eniyan se waa si ìmúsẹ.
O tun wa gbosuba fun aarẹ Buhari nipa awọn ohun amayedẹrun bi ipese irinna ọkọ oju-irin ati eto idagbsoke oju popo ti ijọba rẹ gunle lati mu idẹrun ba gbogbo ọmọ orilẹ ede Naijiria, o tun wa rọ aarẹ Buhari lati pese omi ẹrọ igbalode fun ẹkun wọn..
Leave a Reply