Take a fresh look at your lifestyle.

Nàìjíríà, Saudi Arabia fọwọ́sowọ́pọ̀ láti gbógun ti ìpaniláyà àgbáyé

Eyitayọ Fauziat Oyetunji

0 323

Nàíjíríà àti Saudi Arabia ti ṣe àdéhùn mofaramọ́ àti ìfọwósowópò láti gbógun ti  ìpániláyà àgbáyé.

Awọn orilẹ -ede mejeeji ṣe adehun naa nigbati Minisita Naijiria fun eto ọrọ okeere, Ọgbẹni Geoffrey Onyeama, gba  Minisita eto ọrọ okeere fun orilẹ-ede Saudi Arabia, Faisal bin Far han Al Saud,l’alejo ninu ọfiisi rẹ, ni Abuja, Naijiria.

Ọgbẹni Onyeama sọ ​​pe, Saudi Arabia ati Naijiria ti jọ ni ajọṣepọ to danmọran ni aimọye ọdun sẹyin, o tun wa tẹnumọ  ipinnu  awọn orilẹ -ede mejeeji lati dojuko ipanilaya, paapaa ni agbegbe Sahel ati awọn apakan miiran ti agbaye.

Lori ibaṣepọ iṣowo laarin awọn orilẹ -ede mejeeji, Minisita fun ọrọ okeere orilẹ-ede Naijiria, fihan kedere pe Naijiria ati Saudi Arabia ti tunbọ tẹra mọ ajọṣepọ eto -ọrọ aje wọn lati ṣe alekun iwọn iṣowo ti o wa laarin awọn orilẹ -ede mejeeji.

Ọgbẹni Onyeama sọ ​​pe, Igbimọ Apapọ  Naijiria ati Saudi Arabia ti gbaradi  lati ṣe alekun iṣowo laarin awọn orilẹ -ede mejeeji.

 

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

button