Ènìyàn méjì- lé- lọ́tà- lélọ́ọ̀dúnrún míràn tún ti ní ààrùn covid
Eyitayọ Fauziat Oyetunji
Ní ọjọ́ àìkú,ọjọ́ kọkàn – dín – lọ́gbọ̀n oṣù kẹjọ,ọdún 2021, àwọn ènìyàn méjì- lé –lọ́tà –lélọ́ọ̀dúnrún míràn tún ti ní ààrùn covid, gẹ́gẹ́ bí ilé – iṣẹ́ tó ń mójútó àjàkálẹ̀ ààrùn ṣe kéde rẹ̀ ní ayélujára wẹ́ẹ́bùù rẹ̀.
Lọwọlọwọ bayii,awọn eniyan ẹgbẹ́rún le ni ọ̀kẹ́ mẹ̀sán abo o le ni ẹ́ẹdógún din ni ọ́ta lelọ́ọ̀dúnrún lo ti ni aarun ọhun, ẹgbẹrun le – lọ̀kẹ́ meje- o- le- ni ẹ̀ta le ni ọ́rin-le-nigba ti gba iwosan,ti eniyan mẹẹrinlá-din-ni-ọ́ta din – lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ́ẹ̀talá si ti jẹpe oluwa ni ipinlẹ mẹrindin- lọgbọn,pẹlu olu –ilu.
Awọn meji – le – lọta –lelọọdunrun wọnyii jẹyọ ni awọn ilu mẹẹdogun – Lagos (igba), Ọyọ (mẹtele-lọgbọn), Kwara (ogbọn), Akwa Ibom(mẹrinle-logun), Ogun (mẹtadin-logun), Delta(mẹẹdogun), Ekiti (mẹẹdogun), Plateau (meje), Rivers(meje), Olu- ilu(marun), Anambra (mẹta), Ẹdo(mẹta), Bayelsa (ẹyọkan), Kaduna (ẹyọkan), Kano (eyọkan).
Leave a Reply