COVID-19: Àwọn ènìyàn mọ̀kan le- lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ́ta míràn tún ti ní ààrùn covid
Eyitayọ Fauziat Oyetunji
Orílè-èdè Nàìjíríà tún ti rí àwọn ènìyàn mọ́kànlé-lẹ́ẹ̀dẹ́gbẹ̀ta míràn tó ní ààrùn covid.
Ile-iṣẹ to n mojuto ajakalẹ aarun (NCDC), lo fi idi eyi mulẹ, ni alẹ ọjọ iṣẹgun lori wẹbu rẹ.
Eniyan mẹta lo jẹpe oluwa nipasẹ aarun ọhun lana.
Gẹgẹ bii ile-iṣẹ ọhun ṣe sọ,awọn eniyan mọkanle-lẹẹdẹgbẹta ọhun wa lati ipinlẹ mẹtala-Lagos (màrún din ni ọ́rin-le-nigba), Rivers (mẹtale-lọgọta), Akwa Ibom (mejile-lọgọta ),Gombe (mejile-logun ),Ogun (mẹjọ), Olu-ilu (mẹrin),Ẹdo (mẹta),Imo (meji) ,Kano (ẹyọkan) ,Nasarawa (ẹyọkan) ,Sokoto (ẹyọkan), Jigawa (ẹyọkan ),Ebonyi (ẹyọkan).
Lọwọlọwọ bayii, awọn to ti ni aarun ọhun ti jẹ ọ̀kẹ́ mẹẹdogun- o- le ni- ẹ̀rin le- ni ọ́ta-le-nigba, ẹ̀ẹ́dẹ́gbàta le- ni- ọ̀kẹ́- mẹ̀jọ- o- le- ni èjì –le ni- ọgọ́fà eniyan ti gba iwosan, ti eniyan mẹ̀ta-din-ni-ojì din- ni- ẹgbẹ́ọ̀kànlá si ti jẹpe oluwa.
Leave a Reply