Aarẹ orilẹ ede Naijiria, Muhammadu Buhari ti pada si ilu Abuja, to jẹ olu ilu orilẹ ede Naijiria lẹyin ọjọ mẹjọ ti o lo ni ipinlẹ re iyẹn ipinlẹ Katsina , nibi ti o ti lọ ba wọn se ayẹyẹ ọdun Eid al-Adha ni ilu rẹ to wa ni Daura.
Aarẹ lo asikọ ọ́un lati fi se ifilọlẹ isẹ akanse omi Zobe ni eyi ti yoo maa pese omi fun aadọta miliọnu awọn eniyanni ipinlẹ naa, bakan naa, ni pipese ohun ọgbin ati isẹ agbẹ fun ọkẹaimọye awọn eniyan lati din ìsẹ́ ati òsì kù ni ipinlẹ naa.
ki aarẹ Buhari to kuro ni ipinlẹ katsina, ni o tun lo anfaan ọhun lati pese maalu meji fun awọn agunbanirọ to wa ni ipinlẹ naa.
Bakan naa, ni aarẹ Buhari tun gbalejo awọn oludari ile igbimọ asofin, Femi Gbajabiamila ati awon gomina mejila to wa ni ẹgbẹ oselu APC naa tun wa ki aarẹ ku ọdun ileya ni ilu Daura.
Leave a Reply