Ààbò Orílẹ̀-èdè: Àwọn ọmọ ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin pè fún àfikún owó láti pèsè ààbò tópéye
Eyitayọ Fauziat Oyetunji
Ilé-ìgbìmọ̀ aṣòfin Orílẹ̀-èdè ń bèèrè fún owó tó jọjú díẹ̀ síi, fún Àwọn ọmọ-ogun Nàìjíríà àti àwọn ilé-iṣẹ́ ààbò míràn, láti le kojú ewu rògbòdìyàn tí ó ń da orílẹ̀-èdè náà láàmú.
Abẹnugan ile, Ahmed Lawan pe ipe naa ni ọjọ iṣẹgun, ni ibi apejẹ ounjẹ alẹ kan ti aarẹ Muhammadu Buhari pe, fun gbogbo awọn ọmọ ile-igbimọ aṣofin ati Awọn ọmọ ile Igbimọ Aṣoju.
O tẹnumọ iwulo afikun owo diẹ sii fun aabo, ti si pe akiyesi si pe, “ko si idokowo ti o dara julọ ni orilẹ-ede Naijiria loni ju idokowo lori eto aabo,”pẹlu ireti pe owo aabo yoo gberu diẹ sii ni isuna 2022.
Abẹnugan sọ pe ounjẹ alẹ ọhun kiiṣe ohunjẹ jijẹ bikoṣe igbiyanju lati mu awọn ikọ ijọba lati jọ ṣiṣẹ ni pẹkinpẹki.
Leave a Reply