Take a fresh look at your lifestyle.

COVID-19 : Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà tún ti rí ènìyàn mẹ́rìndín-lọ́gọ́ta míràn

Eyitayọ Fauziat Oyetunji

0 301

Ilé-iṣé tó ń mójútó àjàkálẹ̀ ààrùn ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà (NCDC) sọ pé àwọn ènìyàn mẹ́rìndín-lógún míràn tún ti kún àwọn ẹ̀rin-le-ni-ojì din ni ẹgbẹ́je tó ti ní ààrùn náà tẹ́lẹ̀ lọ́jọ́ àìkú.

Wọn sọ pe awọn mẹrindin-lọgọta ọhun wa jẹyọ ni awọn ilu wọnyii: Eko – mẹtadin-laadọta, olu-ilu –mẹfa,Ogun – meji, ti Gombe si jẹ ẹyọkan pere.

Ile-iṣẹ ọhun sọ pe awọn to ti ni aarun ọhun bayii  jẹ  ẹgbàárin le ni ọ̀kẹ́ mẹ̀jọ o din ni ọ̀kan le ni ojì.

O ṣafikun pe, awọn to ti ni aarun yii, mẹrin miran tun ti gba iwosan ni ile igbatọju jakejado orilẹ-ede.

Ile-iṣẹ naa sọ pe, ẹgbàájì le ni ọ̀kẹ́ mẹ̀jọ o le ni èjì le ni ọ́rin lelọ́ọ̀dúnrún eniyan lo ti gba iwosan bayii,ko si enikankan to jẹpe ọlọrun ni ọjọ kẹrin,oṣu keje yii,ti awọn to ti jẹpe ọlọrun si jẹ ọ̀kan-le-ni-okòó le ni ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ́ọ̀kànlá.

NCDC sọ pe, miliọnu meji ati ọọdunrun eniyan lo ti ṣayẹwo bayii, ninu igba miliọnu awọn ọmọ orilẹ-ede Naijiria.

 

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

button