Take a fresh look at your lifestyle.

Àjọ ECOWAS ṣe ìrántí ayẹyẹ ọdún mẹ̀rindinláá̀dọ́ta tí wọ́n dá àjọ náà sílẹ̀

Ademọla Adepọju

0 283

Àjọ ilẹ Afrika ti a mo si ,Economic Community of West African States (ECOWAS) ti ṣe  ìrántí ayẹyẹ ọdún mẹ̀rindinláá̀dọ́ta ti wọn da àjọ ọ̀hún  silé̀..

Ọjọ́ kejidinlọgbọn  ni won maa n ṣe ayẹyẹ ajodun yii lọdọọdun.

Akori ọdun yii ni wọn pe ni “ Àseyọrí tí ó ju àjàkálẹ̀ ààrùn lọ”  ni eyi ti o faarahan nipa ipa pataki ti  awọn adari ilẹ afirika fihan  lati gbogun ti ajakalẹ aarun,Covid-19  ni ẹkun ti wọn n dari,ni eyi ti wọn tun fi ni aseyọri nipa eto  orọ̀ ajé.

Gẹgẹ bi atẹjade kan lati ajọ ilẹ afirika ti won gbe jade pé , ajakalẹ aarun COVID-19 bá ajọ ECOWAS  wọya ìjà laarin ọdun kan, sibẹ ajọ ECOWAS ti wa lojuna lati mu eto orọ̀ aje wọn bọ̀ sípò.

lọdun mẹ̀rindinláá̀dọ́ta ti wọn da àjọ ọ̀hún  silé̀ niluu Eko lorilẹ ede Naijiria,ni awọn adari ilẹ Afirika fori-kori lati da ajọ ECOWAS silẹ , ni eyi lati lee jẹ ki  ibasepọ ati idagbasoke  to mọnyan lori ba ẹkun ilẹ Afirika ati awọn eniyan wọn .

 

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

button