Abẹnugan ilé ìgbìmọ̀ asojú –sòfin lórílẹ̀ èdè Nàíjíríà , Ahmad Lawan ti ké síta pé orílẹ̀ èdè Nàíjíríà nílò ìrànwọ́ àwọn ọ̀ŕẹ rẹ̀ lágbàáyé láti fòpin sí ìpèníjà tó ń dojúkọ lórí ètò ààbò.
Asofin Lawan sọrọ yii lasiko to n tẹwọgba asoju orilẹ ede UK fun ilẹ Afirika , James Duddridge, ṣi ile igbimọ asofin niluu Abuja , pẹlu asoju orilẹ ede Britain fun orilẹ ede Naijiria, Catriona Laing, pẹlu awọn osisẹ wọn to wa niluu Abuja,olu ilu Naijiria.
Asofin Lawan tun ni “A nigbagbọ pe orilẹ ede Naijiria , ti ṣe gudugudu meje, yaya mẹfa lati daabo bo ẹmi awọn eniyan ati dukia wọn, asiko ti to wayii ki awọn ọrẹ orilẹ Naijiria ni agbaye dide fun iranwọ wa lori eto aabo.
“ Gẹgẹ bi ẹni ti ko nitẹlọrun, a tun fẹ ki ijọba orilẹ ede Britan tubọ ran orilẹ ede Naijiria lọwọ nipa ohun ija ogun, idanilẹkọọ lati lee fopin si iwa ijinipa ati ijinigbe .”
Ademọla Adepọju
Leave a Reply